Ọba Charles ti ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ti bu ọwọ́ lu àwọn òfin tuntun ní ìlú rẹ̀, tí àwọn òfin wọ̀nyí sì sọ pé kò di dandan kí á kọ̀ọ́ sí ara àwọn ayédèrú oúnjẹ (GMO) pé ayédèrú ni wọ́n! Èyí túmọ̀ sí pé ẹni tó ń ra’jà kò le mọ̀ bí oúnjẹ àbáláyé (organic) ni wọ́n ń tà fún òun, tàbí ayédèrú (GMO).

Pẹ̀lú gbogbo ìjàǹbá tí a ti mọ̀ báyi, tí oúnjẹ àti irúgbìn GMO máa ń fà, èyí já sí pé ẹni tí ó bá ń ra ohunkóhun tí ẹnu ń jẹ ní ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì, kò le mọ̀ bóyá ìpalára ni òun ń fi ọwọ́ ara òun rà, tàbí oúnjẹ ànfààní! Ọ̀nà tí àwọn amúnisìn wọ̀nyí ń gbà láti tún ṣe iṣẹ́ ibi wọn nìyí!

Ṣùgbọ́n, ẹ jẹ́ mọ̀ pé Ọba Charles fún’ra rẹ̀ kìí jẹ ohunkóhun tí ó jẹ́ GMO !? Irú ìwà ìkà tí àwọn “alágbayé” (globalists) wọ̀nyí ń ṣe nìyẹn !

Fọ́nrán kan ló fi èyí hàn wá lórí ẹ̀rọ ayélujára ní’bi tí ọkùnrin òyìnbó kan bíi ti Charles fún’ra rẹ̀ ti sòrò lórí oúnjẹ àyípadà àti tí ÀBÁLÁYÉ, tí ó sì tọ́ka sí àgàbàgebè Ọba Charles yi.

Say no to GMO foods in yoruba
IYP say no to GMO seeds / foods

Ó ní kò sí ibi tí Charles ń lọ ní àgbáyé yí tí àwọn olóńjẹ tirẹ̀ kìí tẹ̀lée, tí wọ́n á sì gbé oúnjẹ rẹ̀ dání. Kò s’ohun tó búrú nínú ìyẹn, ṣebí bó ṣe wu’ni l’a ṣe ń ṣe nǹkan ẹni; ṣùgbọ́n ohun tó burú níbẹ̀ ni pé, àwọn olónjẹ Charles kò gbọdọ̀ fi oúnjẹ GMO kankan sáarín oúnjẹ Charles ọ̀ún, tórí ó mọ ewu ń lá tó wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n òun kannáà yí ló sọ pé wọ́n lè ta oúnjẹ GMO ní ìlú òun láì sọ fún oníbarà pé GMO ni o!

Àwa ọmọ-ìbílẹ̀-Yorùbá (Indigenous Yoruba People, I.Y.P), ó ti wá hàn gbangba báyi, pé àwọn “alágbayé” (globalists) amúnisìn wọ̀nyí, kò ní’fẹ́ ẹnikan-kan, ìkórira tí wọ́n ní fún aláwọ̀dúdú kò ṣe é fẹ’nu sọ, kódà wọ́n kórira ara wọn pàápàá.

Gbogbo ohun tí wọ́n ń ṣe wọ̀nyí, wọ́n ti tò ó sílẹ̀, kì í ṣe òní ! Ní ọjọ́ kéjìlélógún oṣù ṣẹrẹ okòó-lé-lẹ́gbàá ọdún, ni Ọba Charles yí ti sọ́, pé, “Àkókò tí a níláti gbé ìgbésẹ̀ nìyí.” Ìgbésẹ̀ kíni o?

Ìgbésẹ̀ láti kó gbogbo ayé papọ̀ sábẹ́ òrùlé kan! Kí wọ́n lè máa jẹgàba lórí àgbáyé, láìṣe Olódùmarè. Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yoruba, D.R.Y), kò sí lára àwọn tí wọ́n máa jẹgàba lé lórí.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.
Ìròyìn Òmìnira Olojoojumọ – Bèrè fún ẹ̀da títí rẹ!

Adúpẹ́ lọ́wọ́ Ẹlẹ́dàá wa, fún ìránṣẹ́ Rẹ̀, Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá tí ó rán sí wa, Olùgbàlà Ìran Yorùbá, láti ṣí wa lójú kí a kúrò lóko ẹrú, kí àwa gẹ́gẹ́bí ọmọ ìbílẹ̀ Yorùbá kí a bọ́sí ògo ayérayé wa, kí á sì máa yin Olódùmarè títí ayé!

Ẹ jẹ́ kí á rántí o, kò gbọdọ̀ sí irúgbìn GMO ní Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá. Ibikíbi tí ẹ bá ti rí ẹni tí ó bá gba irúgbìn yí tàbí ẹni tí ó fún wọn, ẹ bá wa ya àwòrán wọn, àti ẹni tí ó fún wọn, àti ẹni tí ó gbàá, apànìyàn ni àwọn méjèèjì. Ẹ tọ́jú àwọn irúgbìn àbáláyé tó wà lọ́wọ́ yín.